26 láti rọ òjò sí orí ilẹ̀ níbi tí kò sí eniyan,ati ní aṣálẹ̀, níbi tí kò sí ẹnikẹ́ni?
27 Láti tẹ́ aṣálẹ̀ lọ́rùn,ati láti mú kí ilẹ̀ hu koríko?
28 Ṣé òjò ní baba; àbí, baba wo ló sì bí ìrì?
29 Ìyá wo ló bí yìnyín,inú ta ni òjò dídì sì ti jáde?
30 Ó sọ omi odò di líle bí òkúta,ojú ibú sì dì bíi yìnyín.
31 “Ṣé o lè fokùn so ìràwọ̀ Pileiadesi,tabi kí o tú okùn ìràwọ̀ Orioni?
32 Ṣé o lè darí àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀, ní àkókò wọn,tabi kí o ṣe atọ́nà ìràwọ̀ Beari ati àwọn ọmọ rẹ̀?