4 Níbo lo wà, nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀?Bí o bá mọ ìgbà náà, sọ fún mi.
5 Ta ló ṣe ìdíwọ̀n rẹ̀–ṣebí o mọ̀ ọ́n, dá mi lóhùn!Àbí ta ló ta okùn ìwọ̀n sórí rẹ̀?
6 Orí kí ni a gbé ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé,àbí ta ló fi òkúta igun rẹ̀ sọlẹ̀;
7 tí àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ ń jùmọ̀ kọrin,tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọrun sì búsáyọ̀?
8 Ta ló tìlẹ̀kùn mọ́ òkun,nígbà tí ó ń ru jáde,
9 tí mo fi awọsanma ṣe ẹ̀wù rẹ̀,tí òkùnkùn biribiri sì jẹ́ ọ̀já ìgbànú rẹ̀,
10 tí mo sì pa ààlà fún un,tí mo sé ìlẹ̀kùn mọ́ ọn,