6 Orí kí ni a gbé ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé,àbí ta ló fi òkúta igun rẹ̀ sọlẹ̀;
7 tí àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ ń jùmọ̀ kọrin,tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọrun sì búsáyọ̀?
8 Ta ló tìlẹ̀kùn mọ́ òkun,nígbà tí ó ń ru jáde,
9 tí mo fi awọsanma ṣe ẹ̀wù rẹ̀,tí òkùnkùn biribiri sì jẹ́ ọ̀já ìgbànú rẹ̀,
10 tí mo sì pa ààlà fún un,tí mo sé ìlẹ̀kùn mọ́ ọn,
11 tí mo wí pé, ‘Dúró níhìn-ín, o kò gbọdọ̀ kọjá ibẹ̀,ibí ni ìgbì líle rẹ ti gbọdọ̀ dáwọ́ dúró?’
12 Jobu, láti ọjọ́ tí o ti dé ayé,ǹjẹ́ o ti pàṣẹ pé kí ilẹ̀ mọ́ rí,tabi pé kí àfẹ̀mọ́jú mọ́ àkókò rẹ̀,