11 Ṣé o lè gbẹ́kẹ̀lé e nítorí pé agbára rẹ̀ pọ̀,tabi kí o fi iṣẹ́ rẹ sílẹ̀ fún un láti ṣe?
12 Ṣé o ní igbagbọ pé yóo pada,ati pé yóo ru ọkà rẹ̀ wá sí ibi ìpakà rẹ?
13 “Ògòǹgò lu ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ninu ọláńlá rẹ̀,ṣugbọn kò lè fò bí ẹyẹ àkọ̀?
14 Ó yé ẹyin rẹ̀ sórí ilẹ̀,kí ooru ilẹ̀ lè mú wọn,
15 ó gbàgbé pé ẹnìkan le tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ kí wọn sì fọ́,ati pé ẹranko ìgbẹ́ lè fọ́ wọn.
16 Ògòǹgò kò náání àwọn ọmọ rẹ̀,ó ń ṣe sí wọn bí ẹni pé kì í ṣe òun ló bí wọn,kò bìkítà bí wahala rẹ̀ tilẹ̀ já sí asán;
17 nítorí pé Ọlọrun kò fún un ní ọgbọ́n ati òye.