16 Ògòǹgò kò náání àwọn ọmọ rẹ̀,ó ń ṣe sí wọn bí ẹni pé kì í ṣe òun ló bí wọn,kò bìkítà bí wahala rẹ̀ tilẹ̀ já sí asán;
17 nítorí pé Ọlọrun kò fún un ní ọgbọ́n ati òye.
18 Ṣugbọn nígbà tí ó bá ṣetán ati sáré,a máa fi ẹṣin ati ẹni tí ó gùn ún ṣe yẹ̀yẹ́.
19 “Ṣé ìwọ ni o fún ẹṣin lágbára,tí o sì fi agbára ṣe gọ̀gọ̀ sí i lọ́rùn?
20 Ṣé ìwọ lò ń mú kí ó máa ta pọ́nún bí eṣú,tí kíké rẹ̀ sì ń bani lẹ́rù?
21 Ó fẹsẹ̀ walẹ̀ ní àfonífojì,ó yọ̀ ninu agbára rẹ̀,ó sì jáde lọ sí ojú ogun.
22 Kò mọ ẹ̀rù, ọkàn rẹ̀ kì í rẹ̀wẹ̀sì,bẹ́ẹ̀ ni kì í sá fún idà.