19 “Ṣé ìwọ ni o fún ẹṣin lágbára,tí o sì fi agbára ṣe gọ̀gọ̀ sí i lọ́rùn?
20 Ṣé ìwọ lò ń mú kí ó máa ta pọ́nún bí eṣú,tí kíké rẹ̀ sì ń bani lẹ́rù?
21 Ó fẹsẹ̀ walẹ̀ ní àfonífojì,ó yọ̀ ninu agbára rẹ̀,ó sì jáde lọ sí ojú ogun.
22 Kò mọ ẹ̀rù, ọkàn rẹ̀ kì í rẹ̀wẹ̀sì,bẹ́ẹ̀ ni kì í sá fún idà.
23 Ó gbé apó ọfà sẹ́yìn, tí ń mì pẹkẹpẹkẹ, pẹlu ọ̀kọ̀tí ń kọ mànà, ati apata.
24 Ó ń fi ẹnu họlẹ̀ pẹlu ìgboyà ati ìwàǹwára,nígbà tí ipè dún, ara rẹ̀ kò balẹ̀.
25 Nígbà tí fèrè dún, ó kọ, ‘Hàáà!’Ó ń gbóòórùn ogun lókèèrè,ó ń gbọ́ igbe ọ̀gágun tí ń pàṣẹ.