4 Àwọn ọmọ wọn á di alágbára,wọn á dàgbà ninu pápá,wọn á sì lọ, láìpadà wá sọ́dọ̀ àwọn òbí wọn mọ́.
5 “Ta ló fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ lómìniratí ó sì tú ìdè rẹ̀?
6 Mo fi inú pápá ṣe ilé rẹ̀,ilẹ̀ oníyọ̀ sì di ibùgbé rẹ̀.
7 Ó ń pẹ̀gàn ìdàrúdàpọ̀ inú ìlú ńlá,kò gbọ́ ariwo àwọn tí wọn ń fi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ṣiṣẹ́.
8 Ó ń rìn káàkiri àwọn òkè bí ibùjẹ rẹ̀,ó sì ń wá ewéko tútù kiri.
9 “Ṣé ẹfọ̀n ṣetán láti sìn ọ́?Ṣé yóo wá sùn ní ibùjẹ ẹran rẹ lálẹ́?
10 Ṣé o lè so àjàgà mọ́ ọn lọ́rùn ní poro oko,tabi kí ó máa kọ ebè tẹ̀lé ọ?