1 Nígbà náà ni Elifasi, ará Temani, dá Jobu lóhùn, ó ní:
2 “Bí eniyan bá bá ọ sọ̀rọ̀,ṣé kò ní bí ọ ninu?Àbí eniyan ha lè dákẹ́ bí?
3 O ti kọ́ ọpọlọpọ eniyan,o ti fún aláìlera lókun.
4 O ti fi ọ̀rọ̀ gbé àwọn tí wọn ń ṣubú ró,ọ̀rọ̀ rẹ ti fún orúnkún tí ń yẹ̀ lọ lágbára.
5 Ṣugbọn nisinsinyii tí ọ̀rọ̀ kàn ọ́,o kò ní sùúrù;Ó dé bá ọ, ìdààmú bá ọ.