9 Ṣé o lágbára bí èmi Ọlọrun,àbí o lè sán wàá bí ààrá, nígbà tí o bá ń sọ̀rọ̀?
10 Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, fi ọlá ati ìyìn ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́,kí o sì fi ògo ati ẹwà bo ara rẹ bí aṣọ.
11 Fi ibinu rẹ hàn, wo gbogbo àwọn agbéraga,kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
12 Wo gbogbo àwọn agbéraga, kí o sì sọ wọ́n di yẹpẹrẹ,rún àwọn ẹni ibi mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ papọ̀,dì wọ́n ní ìgbèkùn sí ipò òkú.
14 Nígbà náà ni n óo gbà pé,agbára rẹ lè fún ọ ní ìṣẹ́gun.
15 “Wo Behemoti, ẹran ńlá inú omi,tí mo dá gẹ́gẹ́ bí mo ti dá ọ,koríko ni ó ń jẹ bíi mààlúù!