1 Jobu bá dá OLUWA lóhùn ó ní:
2 “Mo mọ̀ pé o lè ṣe ohun gbogbo,kò sì sí ohun tí ó lè da ìpinnu rẹ rú.
3 Ta nìyí tí ń fi ìmọ̀ràn pamọ́ láìní òye?Àwọn ohun tí mo sọ kò yé mi,ìyanu ńlá ni wọ́n jẹ́ fún mi,n kò sì mọ̀ wọ́n.
4 O ní kí n tẹ́tí sílẹ̀,nígbà tí o bá ń sọ̀rọ̀,kí n sì dáhùn nígbà tí o bá bèèrè nǹkan lọ́wọ́ mi.
5 Ìró rẹ ni mo gbọ́ tẹ́lẹ̀,ṣugbọn nisinsinyii mo ti rí ọ;