14 “Ẹni tí ó bá kọ̀tí kò ṣàánú ọ̀rẹ́ rẹ̀kò ní ìbẹ̀rù Olodumare.
15 Ṣugbọn, ẹ̀yin arakunrin mi,ẹlẹ́tàn ni yín, bíi odò àgbàrátí ó yára kún,tí ó sì tún yára gbẹ,
16 tí yìnyín bo odò náà tóbẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣókùnkùn,tí yìnyín ńláńlá sì farapamọ́ sibẹ,
17 ṣugbọn ní àkókò ooru, wọn a yọ́,bí ilẹ̀ bá ti gbóná,wọn a sì gbẹ.
18 Àwọn oníṣòwò tí ń lo ràkúnmíyà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n ń wá omi kiriwọ́n kiri títí wọ́n fi ṣègbé ninu aṣálẹ̀.
19 Àwọn oníṣòwò Temani ń wò rá rà rá,àwọn ọ̀wọ́ èrò Ṣeba sì dúró pẹlu ìrètí.
20 Ìrètí wọn di òfonítorí wọ́n ní ìdánilójú.Wọ́n dé ibi tí odò wà tẹ́lẹ̀,ṣugbọn òfo ni wọ́n bá.