2 “Bí ó bá ṣeéṣe láti wọn ìbànújẹ́ mi,tí a bá sì le gbé ìdààmú mi lé orí ìwọ̀n,
3 ìbá wúwo ju yanrìn etí òkun lọ.Ìdí nìyí tí mo fi ń fi ìtara sọ̀rọ̀.
4 Ọfà Olodumare wọ̀ mí lára,oró rẹ̀ sì mú mi.Ọlọrun kó ìpayà bá mi.
5 Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó a máa kétí ó bá rí koríko jẹ?Àbí mààlúù a máa dúntí ó bá ń wo oúnjẹ rẹ̀ nílẹ̀?
6 Ǹjẹ́ ohun tí kò dùn ṣe é jẹláì fi iyọ̀ sí i?Tabi, adùn wo ní ń bẹ ninu funfun ẹyin?
7 Irú oúnjẹ bẹ́ẹ̀ kì í wù mí í jẹ,Ìríra ni jíjẹ rẹ̀ jẹ́ fún mi.
8 “Ìbá ti dára tó, kí Ọlọrun mú ìbéèrè mi ṣẹ,kí ó fún mi ní ohun tí ọkàn mi ń fẹ́.