21 Bẹ́ẹ̀ ni ẹ rí sí mi nisinsinyii.Ẹ rí ìdààmú mi, ẹ̀rù bà yín.
22 Ǹjẹ́ mo tọrọ ẹ̀bùn lọ́wọ́ yín?Tabi mo bẹ̀ yín pé kí ẹ mú ninu owó yín,kí ẹ fi san àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí mi?
23 Ǹjẹ́ mo bẹ̀ yín pé kí ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá;tabi pé kí ẹ rà mí pada kúrò lọ́wọ́ aninilára?
24 “Ó dára, mo gbọ́, ẹ wá kọ́ mi,ẹ ṣàlàyé ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ṣẹ̀ fún mi;n óo sì dákẹ́ n óo tẹ́tí sílẹ̀.
25 Lóòótọ́ ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní agbára,ṣugbọn kí ni ẹ̀ ń bá mi wí lé lórí.
26 Ẹ rò pé mò ń fi ọ̀rọ̀ ṣòfò lásán ni?Kí ni ẹ̀ ń dásí ọ̀rọ̀ èmi onírora sí?
27 Ẹ tilẹ̀ lè ṣẹ́ gègé lórí ọmọ òrukàn,ẹ sì lè díye lé ọ̀rẹ́ yín.