7 Díẹ̀ ni ọrọ̀ tí o ní tẹ́lẹ̀ yóo jẹ́lára ohun tí Ọlọrun yóo fún ọ ní ọjọ́ iwájú.
8 “Mo bẹ̀ ọ́, lọ wádìí nípa ìgbà àtijọ́,kí o ṣe akiyesi ìrírí àwọn baba wa.
9 Nítorí ọmọde ni wá,a kò mọ nǹkankan,ọjọ́ ayé wa sì dàbí òjìji.
10 Àwọn ni wọn óo kọ́ ọ,tí wọn óo bá ọ sọ̀rọ̀,tí wọn óo sì fún ọ ní ìmọ̀ràn ninu òye wọn.
11 “Ṣé koríko etídò le hù níbi tí kò sí àbàtà?Tabi kí èèsún hù níbi tí kò sí omi?
12 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ nígbà tí ó bá ń tanná lọ́wọ́,yóo rọ ṣáájú gbogbo ewéko,láìjẹ́ pé ẹnikẹ́ni gé e lulẹ̀
13 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ ẹni tíó gbàgbé Ọlọrun rí;ìrètí ẹni tí kò mọ Ọlọrun yóo parun.