25 “Ọjọ́ ayé mi ń sáré lọ tete,kò sí ẹyọ ọjọ́ kan tí ó dára ninu wọn.
26 Wọ́n sáré kọjá lọ bíi koríko ojú omi,bí ẹyẹ idì tí ń fò fẹ̀ẹ̀ lọ bá ohun tí ó fẹ́ pa.
27 Bí mo bá sọ pé kí n gbàgbé ìráhùn mi,kí n sì tújúká;kí n má ronú mọ́;
28 ẹ̀rù ìrora mi á bẹ̀rẹ̀ sí bà mí,nítorí mo mọ̀ pé o kò ní gbà pé n kò dẹ́ṣẹ̀.
29 Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá mi lẹ́bi,kí ni mo tún ń ṣe wahala lásán fún?
30 Ọṣẹ yòówù tí mo lè fi wẹ̀,kódà kí n fi omi yìnyín fọ ọwọ́,
31 sibẹ o óo tì mí sinu kòtò ìdọ̀tí.Kódà n óo di ohun ìríra sí aṣọ ara mi.