1 O SI ṣe lẹhin igbati ọdun yipo, li akokò ti awọn ọba lọ si ogun; Joabu si gbé agbara ogun jade, o si ba ilu awọn ọmọ Ammoni jẹ, nwọn si wá, nwọn si do tì Rabba. Ṣugbọn Dafidi duro ni Jerusalemu. Joabu si kọlù Rabba o si pa a run.
2 Dafidi si gbà ade ọba wọn kuro lori rẹ̀, o si ri i pe o wọ̀n talenti wura kan, okuta iyebiye si wà lara rẹ̀; a si fi de Dafidi li ori: o si kó ikogun pipọpipọ lati inu ilu na wá.
3 O si kó awọn enia ti o wà nibẹ jade wá, o si fi ayùn ati irin mimu ati ãke ké wọn. Aní bayi ni Dafidi ṣe si gbogbo ilu awọn ọmọ Ammoni. Ati Dafidi ati gbogbo awọn enia pada bọ̀ si Jerusalemu.
4 O si ṣe lẹhin eyi li ogun si de ni Geseri pẹlu awọn ara Filistia; li akokò na ni Sibbekai ara Huṣa pa Sippai, ti inu awọn ọmọ òmiran: a si tẹ ori wọn ba.
5 Ogun si tun wà pẹlu awọn ara Filistia; Elhanani ọmọ Jairi si pa Lahamu arakunrin Goliati ara Gati, igi ọ̀kọ rẹ̀ si dabi ìti awunṣọ.
6 Ogun si tun wà ni Gati, nibiti ọkunrin gigun kan gbe wà, ika ati ọmọ-ẹsẹ ẹniti o jẹ mẹrinlelogun, mẹfa li ọwọ kọkan, ati mẹfa li ẹṣẹ kọkan, a si bi i pẹlu fun òmiran.
7 Ṣugbọn nigbati o pe Israeli ni ija, Jonatani ọmọ Ṣimea arakunrin Dafidi pa a.
8 Awọn wọnyi li a bi fun òmiran ni Gati; nwọn si tipa ọwọ Dafidi ṣubu, ati ipa ọwọ awọn iranṣẹ rẹ̀.