20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò,Ó sì ra àwọn àgbààgbà ní iyè.
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́là,Ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá,Ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;Òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
24 Òun a gba àyà olú àwọn ènìyàn aráyé,A sì máa mú wọn wọ́ kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀,Òun a sì máa mú wọn tàsé ìrìn bí ọ̀mùtí.