Jóòbù 19 BMY

Jóòbù Fún Bílídádì Ní Èsì

1 Ígbà náà ni Jóòbù dáhùn, ó sì wí pé:

2 “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyàjẹ mí, tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ mi ní ìjàǹjá?

3 Ìgbà mẹ́wàá ní ẹ̀yin ti ń gàn mí;ojú kò tìyín tí ẹ fi jẹ mí níyà.

4 Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo sìnà nítòótọ́,ìsìnà mi wà lára èmi tìkáarami.

5 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si milórí nítòótọ́, tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,

6 Kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni óbì mí ṣubú, ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.

7 “Kiyè sì í, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára;’ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi;mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdajọ́.

8 Ó sọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le èkọjá, Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.

9 Ó ti bọ́ ògo mi,ó sì sí adé kúrò ní orí mi.

10 Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo,ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.

11 Ó sì tinábọ ìbínú rẹ̀ sími,ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.

12 Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi, wọ́nsì mọ odi yí mi ká, wọ́n sì yíàgọ́ mi ká.

13 “Ó mú àwọn arákùnrin mi jìn nàsí mi réré, àti àwọn ojúlùmọ̀ midi àjèjì sí mi pátapáta.

14 Àwọn alájọbí mi fà sẹ́yìn, àwọnafaramọ́ ọ̀rẹ́ mi sì di onígbàgbé mi.

15 Àwọn ará inú ilé mi àti àwọnìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì;èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.

16 Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá milóhùn; mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.

17 Ẹ̀mí mi sú àyà mi, àti òòrun misú àwọn ọmọ inú ìyá mi.

18 Àní àwọn ọmọdé kùnrin fi míṣẹ̀sín: Mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.

19 Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mikórìíra mi, àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.

20 Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ẹran ara mi, mo sì bọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.

21 “Ẹ ṣáànú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi,ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.

22 Nitorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bíỌlọ́run, tí ẹran ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?

23 “Áà! Ìbáṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ minísinsìn yìí, ìbáṣepé a le dà á sínú ìwé!

24 Kí a fi kálàmú irin àti ti òjé kọwọ́n sínú àpáta fún láéláé.

25 Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáùndè miń bẹ láàyè àti pe òun ni yóò dìdedúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;

26 Àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ arami run, síbẹ̀ láìsí ẹran ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,

27 Ẹni tí èmi ó rí fún ara mi, tí ojúmi ó sì wo, kì sì íṣe tiẹlòmìíràn; ọkàn mi sì dákú ní inú mi.

28 “Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘àwa ó ti lépa rẹ̀ tó!Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a ṣáà rí ní ọwọ́ rẹ̀,’

29 Kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù; nítorí ìbínú níímú ìjìyà wá nípa ìdàKí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”