Jóòbù 37 BMY

Ọlọ́run Kì í Pọ́n Ni Lójú Láìnídìí

1 “Ayà sì fò mi si èyí pẹ̀lú, ósì kúro ní ìpò rẹ̀.

2 Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìróohùn rẹ̀, àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.

3 Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo,Mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.

4 Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná Òun kan fọ̀ramúramù; ó sì fi ohùn ọláńlárẹ̀ sán àrá; òhun kì yóò sì dáàrá dúró nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.

5 Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá níọ̀nà ìyanu; ohùn ńláńlá ni íṣe tí àwa kò le mọ̀.

6 Nítori tí ó wí fún Sínóó pé, Ìwọ rọ̀sílẹ̀ ayé, àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, àti fún òjò ńlá agbára rẹ̀.

7 Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kígbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀ó sì tún dá olúkúlùkù ẹ̀nìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀

8 Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inúihò lọ, wọn a sì wà ni ipò wọn.

9 Láti ìhà gúsù ni ìjì àjàyíká tí jádewá, àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọ̀sánmọ̀ ká.

10 Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fí ìdí-omi fúnni, ibú-omi á sì sún kì.

11 Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ múàwọ̀sánmọ̀ wúwo, a sì túàwọ̀sánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.

12 Àwọn wọ̀nyí i káàriri nípà ìlànàrẹ̀, kí wọn kí ó lé ṣe ohunkohuntí ó pa láṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.

13 Ó mú àwọ̀sánmọ̀ wá, ìbá ṣẹ fúnìkìlọ̀, tàbí omi wá sí ayé láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.

14 “Jóòbù, dẹtí sílẹ̀ sí èyí; dúró jẹ́ẹ́ kío sì ro iṣẹ́ ìyanu Ọlọ́run.

15 Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run sọwọ́n lọ́jọ̀, tí ó sì mú ìmọ́lẹ̀ àwọ̀sánmọ̀ rẹ̀ dán?

16 Ìwọ mọ ti àwọ̀sánmọ̀ í fòó lọ,iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀?

17 Aṣọ rẹ̀ ti máa gbóná, nígbà tí ó fiatẹ́gùn ìhà gúsù mú ayé dákẹ́.

18 Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ódúró sinsin, tí ó sì dàbí dígi tí ó yọ̀ dà?

19 “Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un;nítorí pé àwa kò le ílàdí ọ̀rọ̀ nítorí òkùnkùn wa.

20 A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́sọ̀rọ̀? Tàbí ẹnìkan lèwí pé, ìfẹ́ mi ni pé kí a gbémi mù?

21 Ṣibẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò ríoòrùn tí ń dán nínú àwọ̀sánmọ̀,ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ń kọjá, a sì fẹ́ wọn mọ́.

22 Góòlù dídán ti inú ìhà àríwá jádewá; lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ọláńlá ẹ̀rùn ńlá.

23 Nipa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀; ó ré kọjá ní ipá; nínúìdájọ́ àtí títí bi oun kì í ba ẹ̀tọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òtítọ́ jẹ́.

24 Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rùrẹ̀; òun kì í se ojú sájú ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́n ní ayé?”