20 Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lúìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iyeọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
21 Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀;nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
22 O kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrònínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápákan fún idà.
23 Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé,níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
24 Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú unbẹ̀rù, wọ́n ó sì sẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ímúra ogun.
25 Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdìsí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmáarè,
26 Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn giga, àní fiìké kòóko àpáta rẹ̀ tí ó nipọn kọlù ú.