1 Ígbà náà ni Bílídádì, ará Ṣúà, dáhùn, ó sì wí pé:
2 “Nígbà wo ni ẹ̀yin yóò tó fi ìdí ọ̀rọ̀tì; ẹ rò ó, nígbẹ̀yìn rẹ̀ ni àwa ó tó máa sọ
3 Nítorí kí ni a ṣe ń kà wá sí bíẹranko, tí a sì ń kà wá si bí ẹni ẹ̀gàn ní ojú yín?
4 Ìwọ fa ara rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ nínúìbínú rẹ̀; kí a ha kọ ayé sílẹ̀nítorí rẹ̀ bi? Tàbí kí a sí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀?