5 “Àwọn aláìlágbára ti iṣà òkúwárìrì, lábẹ́ omi pẹ̀lú àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
6 Ìhòòhò ni ipò òkú níwájú Ọlọ́run,ibi ìparun kò sí ní ibojì.
7 Òun ní o nà ìhà àríwá ọ̀run ní ibiòfùrufú, ó sì fi ayé rọ̀ ní ojú òfo.
8 Ó di omi pọ̀ nínú ìkùùkù àwọsánmọ̀rẹ̀ tí ó nípọn; àwọsánmọ̀ kò sì ya nísàlẹ̀ wọn.
9 Ó sì fa ojú ìtẹ́ rẹ̀ sẹ́yìn, ó sì tẹàwọsánmọ̀ rẹ̀ sí i lórí.
10 Ó fi idẹ yí omi òkun ká, títí déààlà ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn.
11 Ọ̀wọ̀n òpó ọ̀run wárìrì, ẹnu sì yàwọ́n sì ìbàwí rẹ̀.