4 Ètè mi kì yóò sọ̀rọ̀ èké, Bẹ́ẹ̀ niahọ́n mi kì yóò sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
5 Kí a má ríi pé èmi ń dá yín láre;títí èmi ó fi kú, èmi kì yóò sí ìwà òtítọ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi.
6 Òdodo mi ni èmi dìmú ṣinṣin,èmi kì yóò sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́; àyàmi kì yóò sì gan ọjọ́ kan nínú ọjọ́ ayé mi.
7 “Kí ọ̀ta mi kí ó dàbí ènìyànbúburú, àti ẹni tí ń dìde sími kí ó dàbí ẹni aláìsòdodo.
8 Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè,nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?
9 Ọlọ́run yóò ha gbọ́ àdúrà rẹ̀,nígbà tí ìpọ́jú bá dé sí i?
10 Òun ha le ní inú dídùn sí Olódùmarè?Òun ha lé máa képe Ọlọ́run nígbà gbogbo?