5 Nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi,nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
6 Nígbà tí èmi fi òrí àmọ́ n wẹ ìsísẹ̀ mi,àti tí àpata ń tú ìsàn òróró jáde fún mi wá.
7 “Nígbà tí mo jáde la àárin ìlú lọ síẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
8 Nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rími, wọ́n sì sápamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹṣẹ̀ wọn;
9 Àwọn ọmọ aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sí sọ,wọn a sì fí ọwọ́ wọn lé ẹnu;
10 Àwọn ọmọ ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọnsì lẹ̀mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súrefún mi,àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi;