9 Àwọn ọmọ aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sí sọ,wọn a sì fí ọwọ́ wọn lé ẹnu;
10 Àwọn ọmọ ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọnsì lẹ̀mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súrefún mi,àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi;
12 Nítorí mo gbà talákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́,àti aláìní baba, tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmisì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́mi dà bí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹṣẹ̀fún amúkùnún.