19 Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀,èmi sì dàbí eruku àti eérú.
20 “Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run ṣùgbọ́n,ìwọ kò dámi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
21 Ìwọ padà di ẹni ìkà sími; ọwọ́agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
22 Ìwọ gbémi sókè sí inú ẹ̀fúùfù,ìwọ múmi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátapáta.
23 Èmi sáà mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọsínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
24 “Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóòha na ọwọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubu rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
25 Èmi kò ha sunkún bí fún ẹni tí ówà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún talákà bí?