28 Èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn Onidàájọ́ níbẹ̀wò. Nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.
29 “Bí ó bá ṣepé mo yọ̀ sì ìparun ẹnití ó korìíra mi. Tàbí bí mo bá sì gbéra sókè, nígbà tí ibi bá a.
30 Bẹ́ẹ̀ èmí kò sì jẹ ẹnu mi ki ó ṣẹ̀nípa fífi ègún sí ọkàn rẹ̀.
31 Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bálè wí pé, ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?
32 (Àléjò kò wọ̀ ni ìgboro rí; èmí síìlẹ̀kùn mi sílẹ̀ fún èrò.)
33 Bí mo bá bò ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́lẹ̀ bí Ádámù,ni pápá, ẹ̀bi mi mọ́ ni àyà mi.
34 Ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ ènìyàn ni mo ha bẹ̀rù bí?Tàbí ẹ̀gan àwọn ìdílé ní ń bà mí ní ẹ̀rù?Tí mo fi p'ẹnu mọ́, tí èmí kò sì fi jáde sóde?