7 Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà,gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
8 “Sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní èmi lè máa ṣe àwárí,ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi lè máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
9 Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí,ohun ìyanu láìní iye.
10 Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayétí ó sì ń rán omi sí ilẹ̀ẹ́lẹ̀.
11 Láti gbé àwọn orilẹ̀ èdè lékèkí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
12 Ó yí ìmọ̀ àwọn alárèékérekè po,bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdàwọ́lé wọn sẹ.
13 Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú arékerekè ara wọn,àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tari ṣubú ní ògèdèǹgbé.