20 Wọ́n já lulẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lée;wọ́n débẹ̀, wọ́n sì dààmú.
21 Ǹjẹ́ nísinsìn yìí, ẹ̀yin dàbí wọn;ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
22 Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá,tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
23 Tàbí, ẹgbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni,tàbí, ẹrà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì.’?
24 “Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti sìnà.
25 Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tóṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbàwí yín já sí?
26 Ẹ̀yin ṣè bí ẹ ó bá ọ̀rọ̀àti ohùn ẹnu tí ó takú wí tí ó dà bí afẹ́fẹ́.