9 Ọ̀tá wí pé,‘N óo lé wọn, ọwọ́ mi yóo sì tẹ̀ wọ́n;n óo pín ìkógun,n óo sì tẹ́ ìfẹ́ ọkàn mi lọ́rùn lára wọn.N óo fa idà mi yọ,ọwọ́ mi ni n óo sì fi pa wọ́n run.’
10 Ṣugbọn o fẹ́ afẹ́fẹ́ lù wọ́n,òkun sì bò wọ́n mọ́lẹ̀,wọ́n rì bí òjé ninu ibú ńlá.
11 “Ta ló dàbí rẹ OLUWA ninu àwọn oriṣa?Ta ló dàbí rẹ, ológo mímọ̀ jùlọ?Ẹlẹ́rù níyìn tíí ṣe ohun ìyanu.
12 O na ọwọ́ ọ̀tún rẹ,ilẹ̀ sì yanu, ó gbé wọn mì.
13 O ti fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ṣe amọ̀nà àwọn eniyan rẹ tí o rà pada,o ti fi agbára rẹ tọ́ wọn lọ sí ibùgbé mímọ́ rẹ.
14 Àwọn eniyan ti gbọ́, wọ́n wárìrì,jìnnìjìnnì sì dà bo gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ Filistini.
15 Ẹnu ya àwọn ìjòyè Edomu,ojora sì mú gbogbo àwọn olórí ní ilẹ̀ Moabu,gbogbo àwọn tí ń gbé Kenaani sì ti kú sára.