6 Bí ìgbéraga rẹ̀ tilẹ̀ ga, tí ó kan ọ̀run,tí orí rẹ̀ kan sánmà,
7 yóo ṣòfò títí lae bí ìgbọ̀nsẹ̀ ara rẹ̀,àwọn tí wọ́n mọ̀ ọ́n yóo bèèrè pé, ‘Níbo ló wà?’
8 Yóo parẹ́ bí àlá,yóo sì di àwátì,yóo pòórá bí ìran tí a rí lóru.
9 Ojú tí ó ti ń rí i tẹ́lẹ̀ kò ní rí i mọ́,ààyè rẹ̀ yóo sì ṣófo.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóo máa wá ojurere àwọn aláìní,wọn yóo sì san ohun tí baba wọn gbà lọ́wọ́ aláìní pada.
11 Bí ó tilẹ̀ dàbí ọ̀dọ́, tí ó lágbára,sibẹ yóo lọ sí ibojì, yóo sì di erùpẹ̀.
12 Bí ọ̀rọ̀ ìkà tilẹ̀ dùn ní ẹnu rẹ̀,tí ó sì fi pamọ́ sí abẹ́ ahọ́n rẹ̀,