5 Ṣugbọn nígbà tí Elihu rí i pé àwọn mẹtẹẹta kò lè fún Jobu lésì mọ́, inú bí i.
6 Ó ní,“Àgbàlagbà ni yín, ọmọde sì ni mí,nítorí náà ni ojú fi ń tì mí,tí ẹ̀rù sì ń bà mí láti sọ èrò ọkàn mi.
7 Mo ní kí ẹ̀yin àgbà sọ̀rọ̀,kí ọ̀rọ̀ yín sì fa ọgbọ́n yọ gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí yín.
8 Ṣugbọn ẹ̀mí tí ó wà ninu eniyan,tíí ṣe èémí Olodumare,ni ó ń fún eniyan ní ìmọ̀.
9 Kì í ṣe àwọn àgbà nìkan ni wọ́n gbọ́n,tabi pé arúgbó nìkan ni ó mọ òye ohun tó tọ́, tó yẹ.
10 Nítorí náà, ‘Ẹ fetí sílẹ̀,kí èmi náà lè sọ èrò ọkàn mi.’
11 “Mo farabalẹ̀ nígbà tí ẹ̀yin ń sọ̀rọ̀,mo fetí sí ọ̀rọ̀ ọgbọ́n yín,nígbà tí ẹ̀ ń ronú ohun tí ẹ fẹ́ sọ,