1 Elihu tún tẹ̀síwájú ninu ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó ní,
2 “Ní sùúrù fún mi díẹ̀, n óo ṣe àlàyé fún ọ,nítorí mo ní ohun kan tí mo fẹ́ gbẹnusọ fún Ọlọrun.
3 N óo gba ìmọ̀ mi láti ọ̀nà jíjìn,n óo sì fi júbà Ẹlẹ́dàá mi, tí ó ní ìmọ̀ òdodo.
4 Nítorí òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ mi;ẹni tí ìmọ̀ rẹ̀ péye ni èmi tí mò ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí.
5 “Ọlọrun lágbára, kì í kẹ́gàn ẹnikẹ́ni,agbára ati òye rẹ̀ pọ̀ gan-an.