9 Nítorí náà mo ṣunkún, gẹ́gẹ́ bí Jáṣérì ṣe ṣunkún,fún àwọn àjàrà Ṣíbínà.Ìwọ Hẹ́ṣíbónì, Ìwọ Élíálẹ̀,mo bomirin ọ́ pẹ̀lú omi ojú!Igbe ayọ̀ lórí àwọn èṣo pípọ́n rẹàti lórí ìkóórè èyí tí o ti mọ́wọ́dúró.
10 Ayọ̀ àti ìdùnnú ni a ti mú kúrònínú ọgbà-igi eléso rẹ;kò sí ẹnìkan tí ó kọrin tàbíkígbe nínu ọgbà-àjàrà:ẹnikẹ́ni kò fún ọtí níbi ìfúntí,nítorí mo ti fi òpin sí gbogbo igbe.
11 Ọkàn mi kérora fún Móábù gẹ́gẹ́ bí i hápù,àní tọkàntọkàn mi fún ìlú Háréṣétì.
12 Nígbà tí Móábù farahàn ní ibi gíga rẹ̀,ó ṣe ara rẹ̀ ní wàhálà lásán;Nígbà tí ó lọ sí ojúbọ rẹ̀ láti gbàdúràòfo ni ó já sí.
13 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa Móábù.
14 Ṣùgbọn ní àkókò yìí Olúwa wí pé: “Láàrin ọdún mẹ́ta gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ìdè ọgbà rẹ̀ ti máa kà á, Ògo Móábù àti àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn rẹ̀ ni a ó kẹ́gàn, àwọn tí ó ṣálà nínú un rẹ̀ yóò kéré níye, wọn yóò sì jẹ́ akúrẹtẹ̀.”