Àìsáyà 65 BMY

Ìdájọ́ Àti Ìgbàlà

1 “Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi;Àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi.Sí àwọn orílẹ̀ èdè tí kò pe orúkọ mi,Ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’

2 Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi sítasí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle,tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára,tí wọ́n sì gbáralé èrò ara wọn

3 àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbolójú ara mi gan an,wọ́n ń rúbọ nínú ọgbàwọ́n sì ń ṣun tùràrí lóríi pẹpẹ bíríkì;

4 wọ́n ń jókòó láàrin ibojìwọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀;tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀,tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;

5 tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi,nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú miiná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.

6 “Kíyèsí i, a ti kọ ọ́ síwájúu mi:Èmi kì yóò dákẹ́, ṣùgbọ́n n ó san ánpadà lẹ́kùn ún rẹ́rẹ́;Èmi yóò san án padà ní itan wọn

7 àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,”ni Olúwa wí.“Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńláwọ́n sì ṣe mí lẹ́gbin ní òkè kékeré,Èmi yóò wọ́n ọ́n sí wọn nítanẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”

8 Ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí òjé sì tún wà nínú àpólà gírépùtí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘má ṣe bà á jẹ́,ohun dáradára sì kù sínú rẹ̀,’bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi;Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.

9 Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jákọ́bù,àti láti Júdà àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n ọn nì;àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn,ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.

10 Ṣárónì yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran,àti àfonífojì Ákò yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran,fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.

11 “Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀tí ẹ sì gbàgbé òkè mímọ́ mi,tí ó tẹ́ tábìlì fún ọrọ̀tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,

12 Èmi yóò yà ọ́ ṣọ́tọ̀ fún idà,àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa;nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn.Mo ṣọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tísílẹ̀Ẹ̀yin ṣe búrurú ní ojú miẹ sì yan ohun tí ó bàmí lọ́kàn jẹ́.”

13 Nítorí náà ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí nìyìí:“Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun;ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin,àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu,ṣùgbọ́n òrùngbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin;àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀,ṣùgbọ́n a ó dójú ti ẹ̀yin.

14 Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrinláti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá,ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókèláti inú ìrora ọkàn yínàti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.

15 Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún; Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sì pa yín,ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òunyóò fún ní orúkọ mìíràn

16 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náàyóò ṣe é nípaṣẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́;Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náàyóò búra nípaṣẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́.Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbéyóò sì farasin kúrò lójú mi.

Àwọn Ọ̀run Tuntún àti Ayé Tuntún

17 “Kíyèsí i, Èmi yóò dáàwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntunA kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́,tàbí kí wọn wá sí ọkàn.

18 Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láénínú ohun tí èmi yóò dá,nítorí èmi yóò dá Jérúsálẹ́mù láti jẹ́ ohun ìdùnnúàti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.

19 Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jérúsálẹ́mùn ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi;ariwo ẹkún àti igbeni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́,

20 “títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀,tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán;ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-únni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé;ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kanni a ó pè ní ẹni ìfibú.

21 Wọn yó kọ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọnwọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èṣo wọn.

22 Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmìíràn láti gbé,tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmìíràn láti jẹ,Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan,bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí;àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́wọn fún ìgbà pípẹ́.

23 Wọn kì yóò ṣe wàhálà lásántàbí kí wọn bímọ tí ọjọ́ iwájú wọnkì yóò sunwọ̀n;nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún,àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.

24 Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn;nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.

25 Ìkookò àti ọ̀dọ́ àgùntàn yóò jẹun pọ̀,kìnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù,ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò.Wọn kì yóò panilára tàbí panirunní gbogbo òkè mímọ́ mi,”ni Olúwa wí.