Àìsáyà 13 BMY

Àsọtẹ́lẹ̀ Kan Sí Bábílónì

1 Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó kan Bábílónìèyí tí Àìṣáyà ọmọ Ámọ́sì rí:

2 Gbé àṣíá ṣókè ní orí òkè gbẹrẹfu,kígbe sí wọn,pè wọ́nláti wọlé sí ẹnu ọ̀nà àwọn Bọ̀rọ̀kìnní.

3 Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi,mo ti pe àwọn jagunjagun miláti gbé ìbínú mi jádeàwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.

4 Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè,gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyànGbọ́, ìdàrúdàpọ̀ láàrin àwọn ìjọba,gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀ èdè! Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọàwọn jagunjagun fún ogun.

5 Wọ́n wá láti ọ̀nà jínjìn réré,láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú un rẹ̀—láti pa gbogbo orílẹ̀ èdè náà run.

6 Pohùnréré, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́tòsí,yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.

7 Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ,ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.

8 Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú,ìrora àti ìpayínkeke yóò dì wọ́n mú,wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí.Ẹnìkín-ín-ní yóò wo ẹnìkejìi rẹ̀ pẹ̀lú ìpayàojú wọn á sìgbinájẹ.

9 Kíyèsí i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínúàti ìrunú gbígbóná—láti sọ ilẹ̀ náà dahoroàti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú un rẹ̀ run.

10 Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run ati ìkójọpọ̀ wọnkò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn.Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ òòrùn yóò di òkùnkùnàti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.

11 Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀,àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ẹ wọn.Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéragaèmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.

12 Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọnju ojúlówóo wúrà lọ,yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà ófírì lọ.

13 Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì;ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun,ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná an rẹ.

14 Gẹ́gẹ́ bí èkùlù tí à ń dọdẹ rẹ̀,gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́,ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ,ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.

15 Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu,gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.

16 Àwọn mọ̀jèsín wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn,gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kóàwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.

17 Kíyèsí i, èmi yóò ru àwọn Mẹ́dísì sókè sí wọn,àwọn tí kò bìkítà fún fàdákàtí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.

18 Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀;wọn kò ní ṣàánú àwọn mọ̀jèsíntàbí kí wọn síjú àánú wo àwọn ọmọdé.

19 Bábílónì, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọbaògo ìgbéraga àwọn ará Bábílónìni Ọlọ́run yóò dojúrẹ̀ bolẹ̀gẹ́gẹ́ bí Sódómù àti Gòmórà.

20 A kì yóò sì gbé ibẹ̀ mọ́ tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran;Árábù kan yóò fi àgọ́ rẹ lélẹ̀ níbẹ̀,Olùsọ́ àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.

21 Ṣùgbọ́n àwọn ohun abẹ̀mí aṣálẹ̀ ni yóò gbé bẹ̀,àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn,níbẹ̀ ni àwọn òwììwí yóò máa gbéníbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́-igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.

22 Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn,àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.