Àìsáyà 51 BMY

Ìgbàlà Ayérayé Fún Ṣíhónì

1 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodoàti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa:Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jádeàti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;

2 ẹ wo Ábúráhámù baba yín,àti Ṣérà, ẹni tó bí i yín.Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni,Èmi sì bùkún un, mo sì sọ́ọ́ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.

3 Dájúdájú, Olúwa yóò tu Ṣíhónì nínúyóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀;Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Ídẹ́nì,gbogbo ìgbòrò rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa.Ayọ̀ àti inúdídùn ni a ó rí nínú rẹ̀,ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.

4 “Tẹ́tí sími, ẹ̀yin ènìyàn mi;gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀ èdè mi:Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá;ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀ èdè.

5 Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan,ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà,àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wásí àwọn orílẹ̀ èdè.Àwọn erékùṣù yóò wò míwọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.

6 Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run,wo ilẹ̀ ní ìṣàlẹ̀ ilẹ̀;Àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín,ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wùàwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin.Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé,òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.

7 “Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun tótọ́,ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyàa yín:Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàntàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.

8 Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ;Ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí Ẹ̀gbọ̀n òwú.Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé,àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”

9 Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbáraÌwọ apá Olúwa;dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì,àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́.Ìwọ kọ́ lo ké Rékábù sí wẹ́wẹ́tí o sì fa ewèlè yẹn ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?

10 Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi òkun bíàti àwọn omi inú ọ̀gbun,Tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìṣàlẹ̀ òkuntó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?

11 Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá.Wọn yóò wọ Ṣíhónì wá pẹ̀lú orin kíkọ;ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo oríi wọn.Ayọ̀ àti inú-dídùn yóò sì bà lé wọnìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.

12 “Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú.Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran-ara,àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,

13 tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ,ẹni tí ó ta àwọn ọ̀runtí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé ṣọlẹ̀,tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́nítorí ìbínú àwọn aninilára,tí wọ́n sì gbọ́kàn lé ipanirun?Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?

14 Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọwọn kò ní kú sínú túbú wọn,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.

15 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,tí ó ń ru òkun ṣókè tó bẹ́ẹ̀ tíìgbì rẹ̀ fi ń pariwo Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

16 Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹmo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí àyè rẹ̀,ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀,àti ẹni tí ó sọ fún Ṣhíónì pé,‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’ ”

Kọ́ọ̀bù Ìbínú Olúwa

17 Jí, jí!Gbéra nílẹ̀ Ìwọ Jérúsálẹ́mù,ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwakọ́ọ̀bù ìbínú rẹ̀,ìwọ tí o ti fà á mu dégẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀fèrè tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀ngbọ̀nọ́n.

18 Nínú gbogbo ọmọ tí ó bíkò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ sọ́nànínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.

19 Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ—ta ni yóò tù ọ́ nínú?Ìparun àti Ìdahoro, ìyàn àti idàta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?

20 Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú;wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà,gẹ́gẹ́ bí ẹtu tí a dé mọ́nú àwọ̀n.Ìbínú Olúwa ti kún inú un wọn fọ́fọ́ọ́fọ́àti ìbáwí Ọlọ́run yín.

21 Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́,tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì

22 Ohun tí Olúwa yín Alágbára jùlọ wí nìyìí,Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn an rẹ̀ mọ́“Kíyèsí i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ọ̀ rẹkọ́ọ̀bù tí ó mú ọ ta gbọ̀ngbọ̀nọ́n;láti inú kọ́ọ̀bù náà, ẹ̀kan ìbínú mi,ni ìwọ kì yóò mu mọ́.

23 Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nnílójú rẹ lọ́wọ́,àwọn tí ó wí fún ọ pé,‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lóríì rẹ.’Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lóríi rẹ̀.”