Àìsáyà 9 BMY

A Bí Ọmọ Kan Fún Wa

1 Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀, kò ní sí ìpòrúurù kan kan mọ́ fún àwọn tí ó wà nínú ìbànújẹ́. Nígbà kan rí ó rẹ ilẹ̀ Sẹbúlúnì sílẹ̀ àti ilẹ̀ Nápítalì pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ iwájú, yóò bu ọ̀wọ̀ fún Gálílì ti àwọn aláìkọlà, ní ọ̀nà òkun, ní ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ Jọ́dánì.

2 Àwọn ènìyàn tí ń rìn nínú òkùnkùnti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá;Lórí àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ òjìji ikú niìmọ́lẹ̀ ti ràn.

3 Ìwọ ti sọ orílẹ̀-èdè di ńlá;wọ́n sì yọ̀ níwájúu rẹgẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ti í yọ ayọ̀ ìkóórè,gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ti í yọ̀nígbà tí à ń pín ìkógun.

4 Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a ṣẹ́gun Mídíánì,ìwọ ti fọ́ ọ túútúúúàjàgà ti ń pa wọ́n lẹ́rù,ọ̀pá tí ó dábùú èjìká wọn,ọ̀gọ aninilára wọn.

5 Gbogbo bàtà jagunjagun tí a ti lò lójú ogunàti gbogbo ẹ̀wù tí a yí nínú ẹ̀jẹ̀,ni yóò wà fún ìjóná,àti ohun èlò iná dídá.

6 Nítorí a bí ọmọ kan fún wa,a fi ọmọkùnrin kan fún wa,ìjọba yóò sì wà ní èjìkáa rẹ̀.A ó sì má a pè é ní: ÌyanuOlùdámọ̀ràn, Ọlọ́run AlágbáraBaba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.

7 Ní ti ìgbòòrò Ìjọba rẹ̀ àti àlàáfíà rẹ̀ ni kì yóò ní ìpẹ̀kun.Yóò jọba lórí ìtẹ́ Dáfídìàti lórí ẹ̀kún un rẹ̀ gbogbo,nípa ìfìdímúlẹ̀ àti ìgbéró rẹ̀,pẹ̀lú òtítọ́ àti òdodoláti ìgbà náà lọ àti títí láéláé.Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogunni yóò mú èyi ṣẹ.

Ìbínú Olúwa Sí Ísírẹ́lì

8 Olúwa ti dojú iṣẹ́ kan kọ Jákọ́bù;Yóò sì wá sórí Ísírẹ́lì.

9 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì mọ̀ ọ́n—Éfáímù àti gbogbo olùgbé Ṣamáríà—tí ó sọ pẹ̀lú ìgbéragaàti gààrù àyà pé.

10 Àwọn bíríkì ti wó lulẹ̀ṣùgbọ́n a ó tún un kọ́ pẹ̀lú òkúta dídán,a ti gé àwọn igi ọ̀pọ̀tọ́ lulẹ̀ṣùgbọ́n igi kédárì ní a ó fí dípò wọn.

11 Ṣùgbọ́n Olúwa fún àwọn ọ̀ta Réṣínì ní agbára láti dojúkọ wọ́nó sì ti rú àwọn ọ̀ta wọn ṣókè.

12 Àwọn Árámínì láti ìlà-oòrùnàti Fílístínì láti ìwọ̀ oòrùnwọ́n si fi gbogbo ẹnu jẹ́ Ìsirẹli runNí gbogbo èyí ìbínú un rẹ̀ kò yí kúròṢùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde ṣíbẹ̀.

13 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tí ì yípadàsí ẹni náà tí ó lù wọ́nbẹ́ẹ̀ ní wọ́n kò wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

14 Nítorí náà ni Olúwa yóò ṣe ké àti orí àti ìrùkúrò ní Ísírẹ́lì,àti Imọ̀-ọ̀pẹ àti koríko-odò ní ọjọ́ kanṣoṣo,

15 Àwọn alàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ni orí,àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.

16 Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí sì wọ́n lọ́nàÀwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.

17 Nítorí náà, Olúwa kì yóò dunnú sí àwọn ọ̀dọ́mọkùnrintàbí kí ó káàánú àwọn aláìní baba àti opó,nítorí pé gbogbo wọn jẹ́ ìkà àti aláìmọ́ Ọlọ́run,ibi ni ó ti ẹnu wọn jáde.Ṣíbẹ̀, fún gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúròọwọ́ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

18 Nítòótọ́ ìkà ń jóni bí iná,ó ń jó àtẹ̀wọ̀n, àtẹ̀gùn run,ó sì ń dáná sun ìgbẹ́tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ń yí lọ sókè ní ọ̀wọ̀n èéfín.

19 Nípaṣẹ̀ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogunilẹ̀ náà yóò di gbígbẹàwọn ènìyàn yóò sì di ohun ìdáná,ẹnìkan kì yóò sì dá arákùnrin rẹ̀ sí.

20 Ní apá ọ̀tún wọn yóò jẹrun,síbẹ̀ ebi yóò sì máa pa wọ́n,ní apá òsì, wọn yóò jẹṣùgbọ́n, kò ní tẹ́wọn lọ́rùn.Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò sì máa jẹ ẹran-ara ọmọ rẹ̀.

21 Mánásè yóò máa jẹ Éfáímù, nígbà tí Éfáímù yóò jẹ Mánásèwọn yóò parapọ̀ dojúkọ Júdà.Ṣíbẹ̀síbẹ̀, ìbínú un rẹ̀ kò yí kúròỌwọ́ọ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.