4 Ọkàn mí dàrú,ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi,tanmọóko tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ ríti wá di ìpayà fún mi.
5 Wọ́n tẹ́ tábìlì,wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká,wọ́n jẹ, wọ́n mu!Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin òṣìṣẹ́,ẹ kún aṣà yín!
6 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi:“Lọ, kí o bojúwòdekí o sì jẹ́ kí ó wá sọ ohun tí ó rí.
7 Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogunàti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin,àwọn agun-kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́tàbí àwọn tí ó gun ràkúnmí,jẹ́ kí ó múra sílẹ̀,àní ìmúra gidigidi.”
8 Báyìí ni alóre náà kígbe,“Láti ọjọ́ dé ọjọ́, Olúwa mi, mo dúró ní ilé ìṣọ́,alaalẹ́ ni mo fi ń wà nípò mi.
9 Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀wá yìínínú kẹ̀kẹ́ ogunàti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin.Ó sì mú ìdáhùn padà wá:‘Bábílónì ti ṣubú, ó ti ṣubú!Gbogbo àwọn ère òrìṣàa rẹ̀ló fọ́nká lórí ilẹ̀!’”
10 Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gúnmọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà,mo sọ ohun tí mo ti gbọ́láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun,láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Ísírẹ́lì.