1 Ní ọjọ́ náà ni Heṣekáyà ṣe àìṣàn dé ojú ikú. Wòlíì Àìṣáyà ọmọ Ámósì sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ohun tí Olúwa wí nìyìí: palẹ̀ iléẹ̀ rẹ mọ́, bí ó ti yẹ nítorí pé ìwọ yóò kú; ìwọ kì yóò dìde àìṣàn yìí.”
2 Heṣekáyà yí ojúu rẹ̀ sí ara ògiri, ó sì gba àdúrà sí Olúwa,
3 “Rántí, Ìwọ Olúwa, bí mo ti rìn pẹ̀lú òtítọ́ níwájúù rẹ, àti bí mo ti fi ọkàn dídúró ṣinṣin ṣe ohun tí ó dára ní ojúù rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni Heṣekáyà sì ṣunkún kíkorò.
4 Lẹ́yìn náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Àìṣáyà wá pé