5 Lẹ́yìn náà ni Àìṣáyà sọ fún Heṣekáyà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun:
6 Àsìkò ń bọ̀ nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin rẹ, àti ohun gbogbo tí àwọn baba rẹ ti kó jọ títí di ọjọ́ òní yóò di kíkólọ sí Bábílónì. Ohun kankan kò ní ṣẹ́kù ni Olúwa wí.
7 Àti díẹ̀ nínú àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ, àwọn ẹ̀jẹ̀ àti ẹran-ara rẹ tí a ó bí fún ọ ni a ó kó lọ, wọn yóò sì di ìwọ̀fà nínú ààfin ọba Bábílónì.”
8 “Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ dára,” ni èsì Heṣekáyà. Nítorí ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Àlàáfíà àti ààbò yóò wà ní Ìgbà ayé tèmi.”