Àìsáyà 45:9-15 BMY

9 “Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà,ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrin àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀.Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé:‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé,‘Òun kò ní ọwọ́?’

10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé‘Kí ni o bí?’tàbí sí ìyá rẹ̀,‘Kí ni ìwọ ti bí?’

11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìíẸni Mímọ́ Ísírẹ́lì, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀:Nípa ohun tí ó ń bọ̀,ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi,tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?

12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayétí ó sì da ọmọnìyàn sóríi rẹ̀.Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀runmo sì kó àwọn agbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta

13 Èmi yóò gbé Kírúsì ṣókè nínú òdodo mi:Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.Òun yóò tún ìlú mi kọ́yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀,ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan,ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”

14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Àwọn èròjà ilẹ̀ Éjíbítì àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kúṣì,àti àwọn Ṣábíáṣì—wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹwọn yóò sì jẹ́ tìrẹ;wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn,wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́.Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀,wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé,‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì sí ẹlòmìíràn;kò sí ọlọ́run mìíràn.’ ”

15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́,Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Ísírẹ́lì