Àìsáyà 56:3-9 BMY

3 Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀mọ́ Olúwa sọ wí pé,“Olúwa yóò yà mí ṣọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.”Àti kí ìwẹ̀fà kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé“Igi gbígbẹ lásán ni mí.”

4 Nítorí pé ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́,tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mití wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin

5 fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹ́ḿpìlì àti àgbàlá rẹ̀ìrántí kan àti orúkọ kantí ó sànju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrinÈmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayétí a kì yóò ké kúrò.

6 Àti àwọn àjèjì tí ó ṣo ara wọn mọ́ Olúwaláti sìn ín,láti fẹ́ orúkọ Olúwaàti láti foríbalẹ̀ fún ungbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—

7 àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mièmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi.Ọrẹ síṣun àti ẹbọ wọnni a ó tẹ́wọ́gbà lóríi pẹpẹ mi;nítorí a ó máa pe ilé mi níilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀ èdè.”

8 Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé—ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Ísírẹ́lì jọ:“Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lúu wọnyàtọ̀ sí àwọn tí a ti kó jọ.”

9 Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú un pápá,ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!