Àìsáyà 58:6-12 BMY

6 “Ǹjẹ́ irú ààwẹ̀ tí mo ti yàn kọ́ ni èyí:láti já gbogbo ẹ̀wọ̀n àìsòdodoàti láti tú gbogbo okùn àjàgà,láti tú gbogbo àwọn ti à ń ni lára sílẹ̀àti láti fọ́ gbogbo àjàgà?

7 Kì í ha á ṣe láti pín oúnjẹ yín fún àwọn tí ebi ń paàti láti pèsè ibùgbé fún àwọn òtòsì tí ń rìn káàkirinígbà tí ẹ bá rí ẹni tí ó wà níhòòhò, láti daṣọ bò ó,àti láti má ṣe lé àwọn ẹ̀jẹ̀ àti ẹran yín sẹ́yìn?

8 Nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ rẹ yóò tàn jáde bí òwúrọ̀àti ìmúláradá rẹ yóò farahàn kíákíá;nígbà náà ni òdodo rẹ yóò sì lọ níwájúù rẹ,ògo Olúwa yóò sì jẹ́ ààbò lẹ́yìn rẹ.

9 Nígbà yìí ni ẹ̀yin yóò pè, tí Olúwa yóò sì dáhùn;ẹ̀yin yóò kígbe fún ìrànlọ́wọ́, òun yóò sì wí pé: Èmi nìyí.“Bí ẹ̀yin bá mú àjàgà aninilára kúrò,pẹ̀lú ìka àléébù nínà àti ọ̀rọ̀ ìṣáátá,

10 àti bí ẹ̀yin bá ná ara yín bí owó nítorí àwọn tí ebi ń patí ẹ sì tẹ́ ìfẹ́ àwọn tí à ń ni lára lọ́rùn,nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ yín yóò ràn nínú òkùnkùn,àti òru yín yóò dàbí ọ̀ṣán-gangan.

11 Olúwa yóò máa tọ́ ọ yín nígbà gbogbo;òun yóò tẹ́ gbogbo àìní ìn yín lọ́rùn ní ilẹ̀ tí òòrùn ń tan ìmọ́lẹ̀yóò sì fún egungun rẹ lókun.Ìwọ yóò sì dàbí ọgbà tí a bomirin dáadáa,àti bí orísun tí omi rẹ̀ kì í tán.

12 Àwọn ènìyàn rẹ yóò tún ahoro ìṣẹ̀ǹbáyé kọ́wọn yóò sì gbé ìpìlẹ̀ àtijọ́-tijọ́ róa ó sì pè ọ́ ní alátúnṣe ògiri tí ó ti wóàti olùmúbọ̀sípò àwọn òpópónà tí ènìyàn gbé inú un rẹ̀.