7 sí Éjíbítì tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀kò wúlò rárá.Nítorí náà mo pè é níRáhábù Aláìlẹ́sẹ̀ nǹkankan.
8 Lọ nísinsìn yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara pátakó fún wọn,tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká,pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
9 Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyànàti ẹlẹ́tanu ọmọ,àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí síìtọ́ni Olúwa.
10 Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé,“Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!”àti fún àwọn wòlíì,“Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́!Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa,ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀,ẹ kúrò ní ọ̀nà yìíẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọwápẹ̀lú Ẹni-Mímọ́ Ísírẹ́lì!”
12 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni-Mímọ́ Ísírẹ́lì wí:“Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀,ẹ gbáralé ìnilárakí ẹ sì gbọ́kànlé ẹ̀tàn,
13 ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọgẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fìtí ó sì wó lójijì, àti ńi ìṣẹ́jú àáyá.