Àìsáyà 44:6-12 BMY

6 “Ohun tí Olúwa wí nìyìíọba Ísírẹ́lì àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun:Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn,lẹ́yin mi kò sí Ọlọ́run kan.

7 Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀.Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú miKí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdíàwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀,àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ aṣọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.

8 Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù.Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọàṣọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ típẹ́típẹ́?Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kanha ń bẹ lẹ́yìn mi?Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”

9 Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán,àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́kò jámọ́ nǹkankan.Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú;wọ́n jẹ́ aláìmọ́kan sí ìtìjú ara wọn.

10 Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère,tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?

11 Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójú tì;àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n.Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sìfi ìdúró wọn hàn;gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú Ìpayà àti àbùkù.

12 Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò,ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú;ó fi òòlù ya ère kan,ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀,Ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un;kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.