15 Nítorí èyí ni ohun tí Ẹni gíga àti ọlọ́lá jùlọ wíẹni tí ó wà títí láé, tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ mímọ́:“Mo ń gbé ní ibi gíga àti ibi mímọ́,ṣùgbọ́n pẹ̀lú ẹni n nì tí ó ní ìròbìnújẹ́ àti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀,láti sọ ẹ̀mí onírẹ̀lẹ̀ náà jíàti láti sọ ẹ̀mí oníròbìnújẹ́ n nì jí.
16 Èmi kì yóò fẹ̀ṣùn kan ni títí láé,tàbí kí n máa bínú ṣá á,nítorí nígbà náà ni ọkàn ọmọnìyàn yóòrẹ̀wẹ̀sì níwájú mièémí ọmọnìyàn tí mo ti dá.
17 Inú bí mi nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀kánjúà rẹ̀;mo fìyà jẹ ẹ́, mo sì fojúù mi pamọ́ ní ìbínúṣíbẹ̀, ó tẹ̀ṣíwájú nínú tinú-mi-ni-n ó ṣe ọ̀nà rẹ̀.
18 Èmi ti rí ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ṣùgbọ́n Èmi yóò wò ó sàn;Èmi yóò tọ́ ọ sọ́nà n ó sì mú ìtùnú tọ̀ ọ́ wá,
19 ní dídá ìyìn sí ètè àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ní Ísírẹ́lì.Àlàáfíà, àlàáfíà fún àwọn tí ó wà lókèèrè àti nítòsí,”ni Olúwa wí, “Àti pé Èmi yóò wo wọ́n sàn.”
20 Ṣùgbọ́n àwọn ìkà dàbí i ríru òkuntí kò le è sinmi,tí ìgbì rẹ̀ ń rú pẹ̀tẹ̀pẹ́tẹ̀ àti ẹrọ̀fọ̀ sókè.
21 “Kò sí àlàáfíà,” ni Ọlọ́run mi wí, “fún àwọn ìkà.”