4 Ṣùgbọ́n pẹ̀lú òdodo ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní,pẹ̀lú òtítọ́ ni yóò ṣe ìpinnufún àwọn aláìní ayé.Òun yóò lu ayé pẹ̀lú ọ̀pá tí ó wà ní ẹnu rẹ̀,pẹ̀lú ooru ẹnu rẹ̀ ni yóò pa àwọn ìkà.
5 Òdodo ni yóò jẹ́ ìgbànú rẹ̀àti òtítọ́ ni yóò ṣe ọ̀já yí ẹ̀gbẹ́ẹ rẹ̀ ká.
6 Ìkookò yóò sì máa bá ọmọ àgùntàn gbé,àmọ̀tẹ́kùn yóò sì sùn ti ewúrẹ́ọmọ màlúù òun ọmọ kìnnìúnàti ọmọ ẹran ó wà papọ̀ọ̀dọ́mọdé yóò sì máa dà wọ́n.
7 Màlúù àti béárì yóò máa jẹun pọ̀,àwọn ọmọ wọn yóò dùbúlẹ̀ pọ̀,kìnnìún yóò sì máa jẹ koríkogẹ́gẹ́ bí akọ màlúù.
8 Ọ̀dọ́mọdé yóò ṣeré lẹ́bàá ihò ọká,Ọmọdé yóò ki ọwọ́ọ rẹ̀ bọ ìtẹ́ẹ paramọ́lẹ̀.
9 Wọn kò ní ṣeni lọ́ṣẹ́ tàbí panirunní gbogbo òkè mímọ́ mi,nítorí gbogbo ayé yóò kún fún ìmọ̀ Olúwagẹ́gẹ́ bí omi ti í bo òkun.
10 Ní ọjọ́ náà, gbòǹgbò Jéésè yóò dúró gẹ́gẹ́ bí àṣíá fún gbogbo ènìyàn, àwọn orílẹ̀ èdè yóò pagbo yí i ká, ibùdó ìsinmi rẹ̀ yóò jẹ́ èyí tí ó lógo.