Àìsáyà 49:1-7 BMY

1 Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù:gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀ èdè jínjìn-nà réré:kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí;láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.

2 Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n,ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pamí mọ́:ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán,ó sì fi mí pamọ́ sínú àpó rẹ̀.

3 Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe,Ísírẹ́lì nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”

4 Ṣùgbọ́n èmi ṣọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán;mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀ mófo.Síbẹ̀ síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sími sì wà lọ́wọ́ Olúwa,èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”

5 Nísinsìn yìí Olúwa wí péẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀láti mú Jákọ́bù padà tọ̀ mí wáàti láti kó Ísírẹ́lì jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú OlúwaỌlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi

6 Òun wí pé:“Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ miláti mú ẹ̀yà Jákọ́bù padà bọ̀ sípòàti láti mú àwọn ti Ísírẹ́lì tí mo ti pamọ́.Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà,kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wásí òpin ilẹ̀ ayé.”

7 Ohun tí Olúwa wí nìyìíOlùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì—sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kóríralọ́wọ́ àwọn orílẹ̀ èdè,sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ:“Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè,àwọn ọmọ ọba yóò ríi wọn yóò sì wólẹ̀,nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olótìítọ́,Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì tí ó ti yàn ọ́.”