8 Ṣíbẹ̀ ṣíbẹ̀, Olúwa, ìwọ ni Baba wa.Àwa ni amọ̀, ìwọ ni ọ̀mọ;gbogbo wa jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
9 Má ṣe bínú kọjá ààlà, Ìwọ Olúwa:Má ṣe rántíi gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa títí láé.Jọ̀wọ́, bojú wò wá, ni a gbàdúrà,nítorí ènìyàn rẹ ni gbogbo wa.
10 Àwọn Ìlú Mímọ́ rẹ ti di aṣálẹ̀;Ṣíhónì pàápàá aṣálẹ̀ ni, Jérúsálẹ́mù ibi ìkọ̀sílẹ̀.
11 Tẹ́ḿpìlì Mímọ́ ológo wa, níbi tí àwọn baba wa ti yìn ọ́,ni a ti fi iná sun,àti ohun gbogbo tí í ṣe ìṣúra wa ti dahoro.
12 Lẹ́yìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí, Olúwa, ìwọó ha sì tún fara rẹ pamọ́ bí?Ìwọ ó ha dákẹ́ kí o sì fìyà jẹwá kọjá ààlà bí?